All Islam Directory
1

Allāhu fi ìyálẹ̀ta búra.

2

Ó tún fi alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú búra.

3

Olúwa rẹ kò pa ọ́ tì, kò sì bínú sí ọ.

4

Dájúdájú ọ̀run lóore fún ọ ju ayé.

5

Dájúdájú láìpẹ́ Olúwa rẹ máa fún ọ ní (oore púpọ̀ ní ọ̀run). Nítorí náà, o sì máa yọ́nú sí i.

6

Ṣé (Allāhu) kò rí ọ ní ọmọ-òrukàn ni? Ó sì fún ọ ní ibùgbé.

7

Ó sì rí ọ ní aláìmọ̀nà (ìyẹn ṣíwájú ìsọ̀kalẹ̀ ìmísí). Ó sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́.1

8

Ó tún rí ọ ní aláìní, Ó sì rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀.

9

Nítorí náà, ní ti ọmọ-òrukàn, má ṣe jẹ gàba (lé e lórí).

10

Ní ti alágbe, má sì ṣe jágbe (mọ́ ọn).

11

Ní ti ìdẹ̀ra Olúwa rẹ, sọ ọ́ jáde.