Gbogbo Islam Library

92 - The Night - Al-Layl

:1

Allāhu fi alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú búra.

:2

Ó tún fi ọ̀sán nígbà tí (ọ̀sán) bá pọ́n búra.

:3

Ó tún fi Ẹni tí Ó dá akọ àti abo búra.1

:4

Dájúdájú ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni iṣẹ́ yín.

:5

Ní ti ẹni tí ó bá tọrẹ, tí ó sì bẹ̀rù (Allāhu),

:6

(tí) ó tún pe ẹ̀san rere (Ọgbà Ìdẹ̀ra) ní òdodo,

:7

A sì máa ṣe iṣẹ́ rere ní ìrọ̀rùn fún un.

:8

Ní ti ẹni tí ó bá yahun, tí ó sì rí ara rẹ̀ lẹ́ni tó rọrọ̀ tayọ ẹ̀san ọ̀run,

:9

(tí) ó tún pe ẹ̀san rere (Ọgbà Ìdẹ̀ra) ní irọ́,

:10

A sì máa ṣe iṣẹ́ aburú ní ìrọ̀rùn fún un.

:11

Dúkìá rẹ̀ kò sì níí rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀ nígbà tí ó bá parun, tí ó já bọ́ (sínú Iná).

:12

Dájúdájú tiWa ni (láti ṣàlàyé) ìmọ̀nà.

:13

Àti pé dájúdájú tiWa ni ọ̀run àti ayé.

:14

Nítorí náà, Mo ti fi Iná tó ń jò fòfò kìlọ̀ fún yín.

:15

Kò sí ẹni tí ó máa wọ inú rẹ̀ àfi olórí burúkú,

:16

ẹni tí ó pe òdodo ní irọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i.

:17

Wọ́n sì máa gbé (Iná) jìnnà sí olùbẹ̀rù (Allāhu),

:18

ẹni tó ń fi dúkìá rẹ̀ tọrẹ, tí ó ń ṣàfọ̀mọ́ (rẹ̀).

:19

Kò sì sí oore ìdẹ̀ra kan tí (ó ní lọ́kàn) láti gbà ní ẹ̀san ní ọ̀dọ̀ ẹnikẹ́ni,

:20

bí kò ṣe pé láti fi wá ojú rere Olúwa rẹ̀, Ẹni Gíga jùlọ.

:21

Láìpẹ́ ó sì máa yọ́nú (sí ẹ̀san rere rẹ̀).