All Islam Directory
1

Sọ pé: “Mo sá di Olúwa àwọn ènìyàn,

2

Ọba àwọn ènìyàn,

3

Ọlọ́hun àwọn ènìyàn,1

4

níbi aburú (Èṣù) oníròyíròyí, olùsásẹ́yìn (fún ẹni tó bá ń dárúkọ Allāhu.

5

(Èṣù ni) ẹni tí ó ń kó ròyíròyí sínú àwọn ọkàn ènìyàn.

6

(Èṣù náà) wà nínú àwọn àlùjànnú àti àwọn ènìyàn.”