114 - Mankind - An-Nās
:1
Sọ pé: “Mo sá di Olúwa àwọn ènìyàn,
:2
Ọba àwọn ènìyàn,
:3
Ọlọ́hun àwọn ènìyàn,1
:4
níbi aburú (Èṣù) oníròyíròyí, olùsásẹ́yìn (fún ẹni tó bá ń dárúkọ Allāhu.
:5
(Èṣù ni) ẹni tí ó ń kó ròyíròyí sínú àwọn ọkàn ènìyàn.
:6
(Èṣù náà) wà nínú àwọn àlùjànnú àti àwọn ènìyàn.”