Gbogbo Islam Library

90 - The City - Al-Balad

:1

Èmi (Allāhu) ń fi ìlú yìíbúra.

:2

Ìwọ sì ní ẹ̀tọ́ sí ìlú yìí (láti jagun nínú rẹ̀).1

:3

Èmi (Allāhu) ń fi òbí àti ohun tó bí búra.

:4

Dájúdájú A ṣẹ̀dá ènìyàn sínú ìṣòro.

:5

Ṣé ó ń lérò pé ẹnì kan kò ní agbára lórí òun ni?

:6

Ó (sì) ń wí pé: “Èmi ti bàná dúkìá ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ (láti fi tako Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -)”

:7

Ṣé ó ń lérò pé ẹnì kan kò rí òun ni?

:8

Ṣé A kò ṣe ojú méjì fún un?

:9

Àti ahọ́n pẹ̀lú ètè méjì (tí A ṣe fún un)?

:10

A sì fi ọ̀nà méjì mọ̀ ọ́n.

:11

Kò sì lọ rin ojú-ọ̀nà orí àpáta tó ṣòroó gùn fún ìgbàlà ẹ̀mí níbi Iná!

:12

Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ ojú-ọ̀nà orí àpáta tó ṣòroó gùn fún ìgbàlà ẹ̀mí?

:13

(Òhun ni) títú ẹrú sílẹ̀ lóko ẹrú.

:14

Tàbí fífún ènìyàn ní oúnjẹ ní ọjọ́ ebi.

:15

(Ẹ lè fún) ọmọ-òrukàn nínú ẹbí,

:16

tàbí mẹ̀kúnnù tí kò ní gá tí kò ní go (olòṣì paraku).

:17

Lẹ́yìn náà, kí ó wà nínú àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n ń gbara wọn níyànjú sùúrù ṣíṣe, tí wọ́n sì tún ń gbara wọn níyànjú àánú ṣíṣe.

:18

Àwọn wọ̀nyẹn ni èrò ọwọ́ ọ̀tún.

:19

Àwọn tó sì ṣàì gbàgbọ́ nínú àwọn āyah Wa, àwọn ni èrò ọwọ́ òsì.1

:20

Wọ́n máa ti àwọn ìlẹ̀kùn Iná pa mọ́ wọn lórí pátápátá.