Gbogbo Islam Library

89 - The Dawn - Al-Fajr

:1

Allāhu fi àfẹ̀mọ́júmọ́ búra.

:2

Ó tún fi àwọn òru mẹ́wàá kan búra.

:3

Ó tún fi n̄ǹkan tí eéjì ń pín geerege àti n̄ǹkan tí eéjì kò pín geerege búra.

:4

Ó tún fi òru nígbà tí ó bá dé búra.

:5

Ǹjẹ́ ìbúra wà nínú ìyẹn fún onílàákàyè?

:6

Ṣé o kò wòye sí bí Olúwa rẹ ti ṣe ọ̀rọ̀ ará ‘Ād,

:7

(ìyẹn àwọn ìran) ’Irọm, àwọn òmìrán,

:8

àwọn tí A kò dá irú wọn mọ́ sínú ìlú?

:9

Àti àwọn Thamūd tí wọ́n gbẹ́ (ilé ìgbé) sínú àpáta nínú àfonúfojì,

:10

àti Fir‘aon eléèkàn (ìyà)?

:11

(Àwọn wọ̀nyí ni) àwọn tó tayọ ẹnu-ààlà nínú ìlú.

:12

Wọ́n sì ṣe ìbàjẹ́ púpọ̀ sínú rẹ̀.

:13

Olúwa rẹ sì rọ̀jò ìyà lé wọn lórí.

:14

Dájúdájú Olúwa rẹ wà ní ibùṣọ́ (iṣẹ́ ẹ̀dá).

:15

Nítorí náà, ní ti ènìyàn, nígbà tí Olúwa rẹ̀ bá dán an wò, tí Ó pọ́n ọn lé, tí Ó sì ṣe ìdẹ̀ra fún un, nígbà náà ó máa wí pé: “Olúwa mi ti pọ́n mi lé.”

:16

Ṣùgbọ́n nígbà tí Ó bá dán an wò, tí Ó gán arísìkí rẹ̀ lé e lọ́wọ́, nígbà náà ó máa wí pé: “Olúwa mi ti yẹpẹrẹ mi.”

:17

Rárá, kò rí bẹ́ẹ̀, bí kò ṣe pé, ẹ̀yin kò ṣàpọ́nlé ọmọ-òrukàn.

:18

Àti pé ẹ̀yin kò gbẹra yín lóǹgbẹ láti fún mẹ̀kúnnù ní oúnjẹ.

:19

Ẹ tún ń jẹ ogún ní ìjẹkújẹ.

:20

Àti pé ẹ nífẹ̀ẹ́ sí dúkìá ní ìfẹ́ púpọ̀.

:21

Rárá, (kò yẹ kó rí bẹ́ẹ̀). Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímì tìtì (tó rún wómúwómú, tí kò sí kòtò, tí kò sí gelemọ),

:22

(tí) Olúwa rẹ dé pẹ̀lú àwọn mọlāika ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ọ̀wọ̀ọ̀wọ́,

:23

ní ọjọ́ yẹn ni wọ́n máa mú iná Jahanamọ wá. Ní ọjọ́ yẹn, ènìyàn yóò rántí (ọ̀rọ̀ ara rẹ̀). Báwo sì ni ìrántí náà ṣe lè wúlò fún un!

:24

Ó máa wí pé: “Yéè, èmi ìbá ti ti (iṣẹ́ rere) síwájú fún ìṣẹ̀mí mi.”

:25

Ní ọjọ́ yẹn, ẹnì kan kò lè fi ìyà jẹ (ẹ̀dá) bí irú ìyà (tí) Allāhu (yóò fi jẹ ẹ́).

:26

Ẹnì kan kò sì lè de (ẹ̀dá) ní ìgbèkùn bí irú ìgbèkùn (tí) Allāhu (yóò fi dè é).

:27

Ìwọ ẹ̀mí olùfọ̀kànbalẹ̀,

:28

padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ní olùyọ́nú, ẹni ìyọ́nú.

:29

Nítorí náà, wọlé sáààrin àwọn ẹrúsìn Mi.

:30

Wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra Mi.