Gbogbo Islam Library
1

(Allāhu) fi sánmọ̀ àti Tọ̄riƙ búra.

2

Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Tọ̄riƙ?

3

Ìràwọ̀ tí ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ń tàn ròrò (ní alẹ́ ni).

4

Kò sí ẹ̀mí kan àfi kí ẹ̀ṣọ́ kan wà fún un (nínú àwọn mọlāika).

5

Nítorí náà, kí ènìyàn wòye sí ohun tí A fi ṣẹ̀dá rẹ̀.

6

Wọ́n ṣẹ̀dá rẹ̀ láti inú omi tó ń tú jáde kọ̀ọ́kọ̀ọ́.

7

Ó ń jáde láti ààrin ìbàdí ọkùnrin àti àwọn ẹfọ́nhà igbá-àyà obìnrin.

8

Dájúdájú Allāhu ni Alágbára lóri ìdápadà rẹ̀

9

ní ọjọ́ tí wọ́n máa ṣe àyẹ̀wò àwọn (iṣẹ́) àṣepamọ́.

10

Nígbà náà, kò níí sí agbára tàbí alárànṣe kan fún un.

11

Allāhu fi sánmọ̀ tó ń rọ òjò ní ọdọọdún búra.

12

Ó tún fi ilẹ̀ tó ń sán kànkàn (fún híhùjáde èso) búra.

13

Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ọ̀rọ̀-ìpínyà (láààrin òdodo àti irọ́).

14

Kì í sì ṣe àwàdà.

15

Dájúdájú wọ́n ń déte gan-an.

16

Èmi náà sì ń déte gan-an.1

17

Nítorí náà, lọ́ra fún àwọn aláìgbàgbọ́. Lọ́ wọn lára sẹ́ fún ìgbà díẹ̀.