Gbogbo Islam Library

80 - He Frowned - `Abasa

:1

Ó fajú ro, ó sì pẹ̀yìndà1

:2

nítorí pé afọ́jú wá bá a.

:3

Kí sì l’ó máa fi mọ̀ ọ́ pé ó ṣeé ṣe kí ó ṣàfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́)

:4

tàbí kí ó gbọ́ ìrántí, kí ìrántí náà sì ṣe é ní àǹfààní?

:5

Ní ti ẹni tí ó ka ara rẹ̀ kún ọlọ́rọ̀,

:6

òun ni ìwọ tẹ́tí sí.

:7

Kò sì sí ẹ̀ṣẹ̀ fún ọ bí kò bá ṣe àfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́).

:8

Ní ti ẹni tí ó sì wá bá ọ, tó ń yára gágá (sí ìrántí, ìyẹn afọ́jú),

:9

tí ó sì ń páyà (Allāhu),

:10

ìwọ kò sì kọbi ara sí i.

:11

Rárá (kò tọ́ bẹ́ẹ̀). Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.

:12

Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó rántí rẹ̀.

:13

(Al-Ƙur’ān) wà nínú àwọn tàkádà alápọ̀n-ọ́nlé,

:14

A gbé e ga, A sì ṣe é ní mímọ́

:15

ní ọwọ́ àwọn òǹkọtíà (ìyẹn, àwọn mọlāika),

:16

àwọn alápọ̀n-ọ́nlé, àwọn ẹni rere.

:17

Wọ́n ti fi ènìyàn gégùn-ún (nípa) bí ó ṣe jẹ́ aláìmoore jùlọ!

:18

Kí sì ni Allāhu fi ṣẹ̀dá rẹ̀?

:19

Nínú àtọ̀ l’Ó ti ṣẹ̀dá rẹ̀. Ó sì pèbùbù (ẹ̀yà-ara) rẹ̀.

:20

Lẹ́yìn náà, Ó ṣe ọ̀nà àtiwáyé ní ìrọ̀rùn fún un.

:21

Lẹ́yìn náà, Ó máa pa á. Ó sì máa fi sínú sàréè.

:22

Lẹ́yìn náà, nígbà tí Allāhu bá fẹ́, Ó máa gbé e dìde.

:23

Rárá o! Ènìyàn kò tí ì ṣe n̄ǹkan tí Allāhu pa láṣẹ fún un.

:24

Nítorí náà, kí ènìyàn wòye sí oúnjẹ rẹ̀.

:25

Dájúdájú Àwa ń rọ òjò ní púpọ̀.

:26

Lẹ́yìn náà, A mú ilẹ̀ sán kànkàn.

:27

A sì mú kóró èso hù jáde láti inú rẹ̀;

:28

àti èso àjàrà àti kànnáfùrù,

:29

àti igi òróró Zaetūn àti dàbínù,

:30

àti àwọn ọgbà tó kún fún igi,

:31

àti àwọn èso (mìíràn) pẹ̀lú ewé tí ẹranko ń jẹ, (A mú wọn hù jáde).

:32

(Wọ́n jẹ́ n̄ǹkan) ìgbádùn fún ẹ̀yin àti àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.

:33

Nígbà tí fífọn sínú ìwo nígbà kejì bá ṣẹlẹ̀,

:34

ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò sá fún arákùnrin rẹ̀,

:35

àti ìyá rẹ̀ àti bàbá rẹ̀,

:36

àti ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀.

:37

Ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn ní ọjọ́ yẹn l’ó ti ní ọ̀ràn tó máa tó o ó rán.

:38

Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn yóò mọ́lẹ̀.

:39

Wọn yó máa rẹ́rìn-ín, wọn yó sì máa dunnú.

:40

Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn ni eruku yó sì bò mọ́lẹ̀.

:41

Òkùnkùn yó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀.

:42

Àwọn wọ̀nyẹn gan-an ni aláìgbàgbọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.