Gbogbo Islam Library

79 - Those who drag forth - An-Nāzi`āt

:1

Allāhu fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà èle gba ẹ̀mí àwọn aláìgbàgbọ́ búra.

:2

Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà ẹ̀rọ̀ gba ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo búra.

:3

Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń yára gágá níbi àṣẹ Rẹ̀ búra.

:4

Ó tún fi àwọn mọlāika tó máa ṣíwájú ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo wọnú Ọgbà Ìdẹ̀ra tààrà búra.

:5

Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń ṣètò nínú sánmọ̀ àti ilé ayé pẹ̀lú àṣẹ Allāhu búra.

:6

Ní ọjọ́ tí ìmìtìtì máa mi gbogbo ayé tìtì.1

:7

Ohun tí ó máa tẹ̀lé e máa ṣẹlẹ̀ tẹ̀lé e.1

:8

Àwọn ọkàn yóò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀ ní ọjọ́ yẹn.

:9

Ojú wọn yó sì wálẹ̀ ní ti ìyẹpẹrẹ.

:10

Wọn yóò wí pé: “Ṣé Wọ́n tún máa dá wa padà sí ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí (bíi tayé ni)?

:11

Ṣé nígbà tí a ti di eegun tó kẹfun tán?”

:12

Wọ́n wí pé: “Ìdápadà òfò nìyẹn nígbà náà (fún ẹni tó pè é ní irọ́.)”

:13

Nítorí náà, igbe ẹyọ kan sì ni.

:14

Nígbà náà ni wọn yóò bára wọn lórí ilẹ̀ gban̄sasa.

:15

Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ (Ànábì) Mūsā ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?

:16

(Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ̀ pè é ní àfonúfojì mímọ́, Tuwā.

:17

Lọ bá Fir‘aon, dájúdájú ó ti tayọ ẹnu-ààlà.

:18

Kí o sì sọ pé: “Ǹjẹ o máa ṣàfọ̀mọ́ ara rẹ (kúrò nínú àìgbàgbọ́) bí?

:19

Kí èmi sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́ dé ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, kí o sì páyà (Rẹ̀).”

:20

Ó sì fi àmì tó tóbi hàn án.

:21

(Àmọ́) ó pè é ní òpùrọ́. Ó sì yapa (rẹ̀).

:22

Lẹ́yìn náà, ó kẹ̀yìn sí i. Ó sì ń ṣiṣẹ́ (takò ó).

:23

Ó kó (àwọn ènìyàn) jọ, ó sì ké gbàjarì.

:24

Ó sì wí pé: “Èmi ni olúwa yín, ẹni gíga jùlọ.”

:25

Nítorí náà, Allāhu gbá a mú pẹ̀lú ìyà ìkẹ́yìn àti àkọ́kọ́ (nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ìkẹ́yìn yìí àti àkọ́kọ́).1

:26

Dájúdájú àríwòye wà nínú ìyẹn fún ẹni tó ń páyà (Allāhu).

:27

Ṣé ẹ̀yin lẹ lágbára jùlọ ní ìṣẹ̀dá ni tàbí sánmọ̀ tí Allāhu mọ?

:28

Allāhu gbé àjà rẹ̀ ga sókè. Ó sì ṣe é ní pípé tó gún régé.

:29

Ó ṣe òru rẹ̀ ní dúdú. Ó sì fa ìyálẹ̀ta rẹ̀ yọ jáde.

:30

Àti ilẹ̀, Ó tẹ́ ẹ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìyẹn.1

:31

Ó mú omi rẹ̀ àti irúgbìn rẹ̀ jáde láti inú rẹ̀.

:32

Àti àwọn àpáta, Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ ṣinṣin.

:33

Ìgbádùn ni fún yín àti fún àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.

:34

Ṣùgbọ́n nígbà tí ìparun ńlá bá dé,

:35

ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò rántí ohun tó ṣe níṣẹ́.

:36

Wọ́n sì máa fi Iná hàn kedere fún (gbogbo) ẹni tó ríran.

:37

Nítorí náà, ní ti ẹni tó tayọ ẹnu-ààlà,

:38

tí ó tún gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé,

:39

dájúdájú iná Jẹhīm, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).

:40

Ní ti ẹni tí ó páyà ìdúró níwájú Olúwa rẹ̀, tí ó tún kọ ìfẹ́-inú fún ẹ̀mí (ara rẹ̀),

:41

dájúdájú Ọgbà Ìdẹ̀ra, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).

:42

Wọ́n ń bi ọ́ léèrè nípa Àkókò náà pé: “Ìgbà wo l’ó máa ṣẹlẹ̀?”

:43

Níbo ni ìwọ wà sí ìmọ̀ rẹ̀ ná?1

:44

Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin ìmọ̀ nípa rẹ̀ wà.

:45

Ìwọ kúkú ni olùkìlọ̀ fún ẹni tó ń páyà rẹ̀.

:46

Ní ọjọ́ tí wọ́n máa rí i, wọn máa dà bí ẹni pé wọn kò gbé ilé ayé tayọ ìrọ̀lẹ́ tàbí ìyálẹ̀ta (ọjọ́) kan.