Gbogbo Islam Library

78 - The Tidings - An-Naba

:1

Nípa kí ni wọ́n ń bíra wọn léèrè ná?

:2

Nípa ìró ìkọ̀kọ̀ ńlá ni,

:3

èyí tí wọ́n ń yapa-ẹnu lórí rẹ̀.

:4

Rárá! Wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.

:5

Lẹ́yìn náà, rárá sẹ́, wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.

:6

Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ìtẹ́ bí,

:7

àti àwọn àpáta ní èèkàn (fún ilẹ̀)?

:8

A sì ṣẹ̀dá yín ní oríṣiríṣi (akọ àti abo).

:9

A ṣe oorun yín ní ìsinmi.

:10

A tún ṣe alẹ́ ní ìbora.

:11

A tún ṣe ọ̀sán ní (àsìkò fún) wíwá ìjẹ-ìmu.

:12

A tún mọ sánmọ̀ méje tó lágbára sókè yín.

:13

A tún ṣe òòrùn ní ìmọ́lẹ̀ tó ń tàn gbòlà.

:14

Àti pé A sọ omi tó ń bọ́ tẹ̀léra wọn kalẹ̀ láti inú àwọn ẹ̀ṣújò

:15

nítorí kí Á lè fi mú kóró èso àti irúgbìn jáde

:16

pẹ̀lú àwọn ọgbà tó kún digbí fún n̄ǹkan oko.

:17

Dájúdájú ọjọ́ ìpínyà, ó ní gbèdéke àkókò kan.

:18

(Ìyẹn ni) ọjọ́ tí wọ́n á fọn fèrè oníwo fún àjíǹde. Ẹ̀yin yó sì máa wá níjọ-níjọ.

:19

Wọ́n sì máa ṣí sánmọ̀ sílẹ̀. Ó sì máa di àwọn ìlẹ̀kùn.

:20

Wọ́n máa mú àwọn àpáta rìn (bọ́ sí àyè mìíràn). Ó sì máa di ahúnpeéná.

:21

Dájúdájú iná Jahanamọ, ó lúgọ sílẹ̀ lójú ọ̀nà.

:22

(Ó jẹ́) ibùgbé fún àwọn alákọyọ.

:23

Wọn yóò máa gbé inú rẹ̀ fún ìgbà gbọọrọ.

:24

Wọn kò níí rí ìtura tàbí ohun mímu kan tọ́wò nínú rẹ̀,

:25

àyàfi omi tó gbóná parí àti àwọnúwẹ̀jẹ̀.

:26

(Ó jẹ́) ẹ̀san tó ṣe wẹ́kú (iṣẹ́ wọn).

:27

Dájúdájú wọn kì í retí ìṣírò-iṣẹ́.

:28

Wọ́n sì pe àwọn āyah Wa ní irọ́ gan-an.

:29

Gbogbo n̄ǹkan sì ni A ti ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú Tírà kan.

:30

Nítorí náà, ẹ tọ́ (ìyà) wò. A ò sì níí ṣe àlékún kan fún yín bí kò ṣe ìyà.

:31

Dájúdájú ìgbàlà wà fún àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu).

:32

Àwọn ọgbà oko àti èso àjàrà,

:33

àti àwọn ọlọ́mọge, tí wọn kò júra wọn lọ lọ́jọ́-orí,

:34

àti ife ọtí tó kún dẹnu (ni ẹ̀san wọn).

:35

Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ irọ́ nínú rẹ̀.

:36

(Ó jẹ́) ẹ̀san láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, (ó sì jẹ́) ọrẹ ní ìbámu sí ìṣírò-iṣẹ́ (wọn).

:37

(Ẹsan náà wá láti ọ̀dọ̀) Olúwa àwọn sánmọ̀, ilẹ̀ àti ohun tó wà láààrin méjèèjì, Àjọkẹ́-ayé. Wọn kò sì ní ìkápá ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ Rẹ̀.

:38

Ọjọ́ tí mọlāika Jibrīl àti àwọn mọlāika (mìíràn) yóò dúró ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́. Wọn kò sì níí sọ̀rọ̀ àfi ẹni tí Àjọké-ayé bá yọ̀ǹda fún. Onítọ̀ún sì máa sọ̀rọ̀ tó máa ṣe wẹ́kú.

:39

Ìyẹn ni ọjọ́ òdodo. Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó mú ọ̀nà tó máa gbà ṣẹ́rí padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ̀ pọ̀n (ní ti ìronúpìwàdà).

:40

Dájúdájú A fi ìyà tó súnmọ́ ṣe ìkìlọ̀ fún yín. Ọjọ́ tí ènìyàn yóò máa wo ohun tí ó tì síwájú, aláìgbàgbọ́ yó sì wí pé: “Yéè, èmi ìbá sì jẹ́ erùpẹ̀, (èmi ìbá là nínú ìyà).”