Gbogbo Islam Library

100 - The Courser - Al-`Ādiyāt

:1

Allāhu fi àwọn ẹṣin tó ń sáré tó ń mí hẹlẹhẹlẹ ní ojú-ogun búra.

:2

Ó tún fi àwọn ẹṣin tí pátákò ẹsẹ̀ wọn ń ṣáná (níbi eré sísá) búra.

:3

Ó tún fi àwọn ẹṣin tó ń kọlu ọ̀tá ẹ̀sìn ní òwúrọ̀ kùtùkùtù búra.

:4

Wọ́n sì fi (pátákò ẹsẹ̀ wọn) tu eruku (ilẹ̀ ọ̀tá) sókè.

:5

Wọ́n tún bẹ́ gìjà pẹ̀lú eruku ẹsẹ̀ wọn sáààrin àkójọ ọ̀tá.

:6

Dájúdájú ènìyàn ni aláìmoore sí Olúwa rẹ̀.

:7

Dájúdájú Allāhu sì ń jẹ́ Ẹlẹ́rìí lórí ìyẹn.

:8

Àti pé dájúdájú ènìyàn le gan-an níbi ìfẹ́ oore ayé.

:9

Ṣé kò mọ̀ pé nígbà tí wọ́n bá tú ohun tó wà nínú sàréè jáde (fún àjíǹde),

:10

tí wọ́n sì tú ohun tó wà nínú igbá-àyà ẹ̀dá síta pátápátá,

:11

dájúdájú Olúwa wọn ni Alámọ̀tán nípa wọn ní Ọjọ́ yẹn?