Gbogbo Islam Library

74 - The Cloaked One - Al-Muddaththir

:1

Ìwọ olùdaṣọbora.

:2

Dìde kí o ṣèkìlọ̀.

:3

Olúwa rẹ sì ni kí o gbé títóbi fún.

:4

Aṣọ rẹ ni kí o fọ̀ mọ́.

:5

Òrìṣà ni kí o jìnnà sí.

:6

Má ṣe tọrẹ nítorí kí o lè rí púpọ̀ gbà.

:7

Olúwa rẹ ni kí o ṣe sùúrù fún.

:8

Nígbà tí wọ́n bá fọn fèrè oníwo fún àjíǹde,

:9

ìyẹn, ní ọjọ́ yẹn, ni ọjọ́ ìnira,

:10

tí kò níí rọrùn fún àwọn aláìgbàgbọ́.

:11

Fi Mí dá ẹni tí Mo dá ní òun nìkan (ìyẹn nínú ikùn ìyá rẹ̀).

:12

Mo sì fún un ní ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ dúkìá

:13

àti àwọn ọmọkúnrin tó ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀.

:14

Mo sì fi àyè ìrọ̀rùn gbá a dáadáa.

:15

Lẹ́yìn náà, ó tún ń jẹ̀rankàn pé kí N̄g ṣe àlékún.

:16

Rárá o! Dájúdájú ó jẹ́ alátakò sí àwọn āyah Wa.

:17

Èmi yóò la ìyà pọ́nkèpọ́nkè bọ̀ ọ́ lọ́rùn (nínú Iná)

:18

Dájúdájú ó ronú (lódì nípa al-Ƙur’ān). Ó sì pinnu (ọ̀rọ̀ kan nínú ẹ̀mí rẹ̀).

:19

Wọ́n sì ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.

:20

Lẹ́yìn náà, Wọ́n tún ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.

:21

Lẹ́yìn náà, ó wò sùn.

:22

Lẹ́yìn náà, ó fajú ro, ó sì dijú mágbárí.

:23

Lẹ́yìn náà, ó pẹ̀yìndà, ó sì ṣègbéraga.

:24

Ó sì wí pé: “Kí ni èyí bí kò ṣe idán àtọwọ́dọ́wọ́.

:25

Kí ni èyí bí kò ṣe ọ̀rọ̀ abara”

:26

Èmi yóò fi sínú iná Saƙọr.

:27

Kí l’ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ iná Saƙọr?

:28

(Saƙọr) kò níí ṣẹ́ ẹ kù, kò sì níí pa á tì.1

:29

Ó máa jó awọ ara di dúdú.

:30

(Àwọn mọlāika) mọ́kàndínlógún ni ẹ̀ṣọ́ rẹ̀.

:31

Àwa kò ṣe ẹnì kan ní ẹ̀ṣọ́ Iná àfi àwọn mọlāika. Àwa kò sì ṣe òǹkà wọn (bẹ́ẹ̀) bí kò ṣe (nítorí kí ó lè jẹ́) àdánwò fún àwọn tó ṣàì gbàgbọ́, àti nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà lè ní àmọ̀dájú àti nítorí kí àwọn tí wọ́n gbàgbọ́ ní òdodo lè lékún ní ìgbàgbọ́ òdodo. (Ó rí bẹ́ẹ̀) nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo má baà ṣeyèméjì àti nítorí kí àwọn tí àrùn wà nínú ọkàn wọn àti àwọn aláìgbàgbọ́ lè wí pé: “Kí ni Allāhu gbà lérò pẹ̀lú àpèjúwe yìí?” Báyẹn ni Allāhu ṣe ń ṣi ẹni tí Ó bá fẹ́ lọ́nà, Ó sì ń tọ́ ẹni tí Ó bá fẹ́ sọ́nà. Kò sì sí ẹni tí ó mọ àwọn ọmọ ogun Olúwa rẹ àfi Òun náà. (Iná Saƙọr) kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe ìrántí fún abara.

:32

Ẹ gbọ́! Allāhu fi òṣùpá búra.

:33

Ó tún fi alẹ́ nígbà tí ó bá lọ búra.

:34

Ó tún fi òwúrọ̀ nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́ búra.

:35

Dájúdájú (iná Saƙọr) ni ọ̀kan nínú (àwọn àdánwò) tó tóbi.

:36

(Ó jẹ́) ìkìlọ̀ fún abara.

:37

Fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti tẹ̀ síwájú tàbí láti fà sẹ́yìn (nínú ẹ̀ṣẹ̀).

:38

Ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan ni onídùúró fún ohun tó ṣe níṣẹ́.

:39

Àyàfi àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.

:40

Wọn yóò máa bira wọn léèrè ọ̀rọ̀ nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra

:41

nípa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pé:

:42

“Kí ni ó mu yín wọ inú iná Saƙọr?”

:43

Wọn yóò wí pé: “Àwa kò sí nínú àwọn olùkírun ni.

:44

Àwa kò sì sí nínú àwọn tó ń bọ́ àwọn mẹ̀kúnnù.

:45

Àwa sì máa ń sọ ìsọkúsọ pẹ̀lú àwọn onísọkúsọ.

:46

Àti pé àwa máa ń pe Ọjọ́ ẹ̀san ní irọ́

:47

títí ikú fi dé bá wa.”

:48

Ìpẹ̀ àwọn olùṣìpẹ̀ kò sì níí ṣe wọ́n ní àǹfààní.

:49

Kí ló mú wọn ná tí wọ́n ń gbúnrí kúrò níbi ìrántí

:50

bí ẹni pé àwọn ni kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tó ń sá lọ,

:51

tó sá fún kìnìhún?

:52

Rárá, ńṣe ni ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú wọn ń fẹ́ kí Á fún òun náà ní Tírà tí ó máa ṣeé tẹ́ han àwọn ènìyàn (bíi ti al-Ƙur’ān).

:53

Rárá. Wọn kò páyà ọ̀run ni.

:54

Ẹ gbọ́! Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.

:55

Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kó rántí rẹ̀.

:56

Wọn kò sì níí rántí (al-Ƙur’ān) àfi tí Allāhu bá fẹ́. (Allāhu) Òun l’a gbọ́dọ̀ bẹ̀rù. Òun l’ó sì ni àforíjìn.