Gbogbo Islam Library

56 - The Inevitable - Al-Wāqi`ah

:1

Nígbà tí Ìṣẹ̀lẹ̀ (Àjíǹde) bá ṣẹlẹ̀,

:2

  • kò sí irọ́ kan nípa ìṣẹ̀lẹ̀ rẹ̀-

:3

ó máa mú (àwọn kan) wálẹ̀ (sínú Iná), ó sì máa gbé (àwọn kan) sókè (nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra).

:4

Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímìtìtì,

:5

àti nígbà tí Wọ́n bá fọ́ àwọn àpáta ní fífọ́ wómúwómú,

:6

  • wọ́n sì máa di eruku àfẹ́dànù -

:7

ẹ̀yin sì máa jẹ́ oríṣi mẹ́ta.1

:8

Àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún?

:9

Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?

:10

Àwọn aṣíwájú sì ni àwọn aṣíwájú.

:11

Àwọn wọ̀nyẹn ni alásùn-únmọ́ (Allāhu)

:12

nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.

:13

Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.

:14

Wọ́n sì kéré nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.

:15

(Wọn yóò wà) lórí ìtẹ́ tí wọ́n fi góòlù hun.

:16

Wọn yóò rọ̀gbọ̀kú sórí rẹ̀, wọn sì máa dojú kọra wọn.

:17

Àwọn ọ̀dọ́kùnrin tí kò níí darúgbó yó sì máa lọ bọ̀ láààrin wọn

:18

pẹ̀lú àwọn ife omi, ohun ìrọmi fẹ̀ǹfẹ̀ àti ife ọtí aládùn láti inú odò kan tó ń ṣàn (káà kiri ọ̀dọ̀ wọn).

:19

Kò níí fọ́ wọn lórí; kò sì níí mú wọn húnrìrà.

:20

Èso tí wọn yóò máa ṣẹ̀ṣà nínú rẹ̀ (tún wà fún wọn).

:21

Àti ẹran ẹyẹ, èyí tí wọ́n ń fẹ́ (yó wà fún wọn).

:22

Àwọn obìnrin ẹlẹ́yinjú ẹgẹ́ (tún wà fún wọn).

:23

Wọ́n dà bí àlúùúlù (òkúta olówó-iye-bíye) tí wọ́n fi pamọ́ sínú apó rẹ̀.

:24

(Ìwọ̀nyí ni) ẹ̀san fún ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́.

:25

Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.

:26

Àyàfi ọ̀rọ̀ àlàáfíà, àlàáfíà.

:27

Àwọn èrò ọwọ́ ọtún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọtún?

:28

(Wọn yóò wà) ní ìdí igi tí kò ní ẹ̀gún,

:29

àti ọ̀gẹ̀dẹ̀ tó so jìgbìnnì,

:30

àti ibòji tó gbòòrò,

:31

àti omi tó ń ṣàn láì dáwọ́ dúró,

:32

àti ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ èso,

:33

tí kò níí já (ní ọ̀dọ̀ wọn), kò sì níí dèèwọ̀ (fún wọn).

:34

(Wọ́n máa wà lórí) ìtẹ́ tí wọ́n gbé sókè.

:35

Dájúdájú Àwa dá (àwọn obìnrin Ọgbà Ìdẹ̀ra) ní ẹ̀dá kan (tó yàtọ̀ sí tayé).

:36

A sì ṣe wọ́n ní wúńdíá,

:37

olólùfẹ́ ọkọ. Wọ́n sì dọ́gba ní ọjọ́ orí.

:38

(Wọ́n wà) fún àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.

:39

Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.

:40

Wọ́n tún pọ̀ nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.1

:41

Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?

:42

(Wọn yóò wà) nínú atẹ́gùn gbígbóná (iná) àti omi tó gbóná parí,

:43

àti ní abẹ́ ibòji eléèéfín dúdú,

:44

kò tutù, kò sì dára.

:45

Dájúdájú wọ́n ti jẹ́ onígbẹdẹmukẹ ṣíwájú ìyẹn.

:46

Wọ́n sì máa ń ṣoríkunkun lórí ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.

:47

Wọ́n sì máa ń wí pé: “Ṣé nígbà tí a bá di òkú, tí a sì di erùpẹ̀ àti egungun, ǹjẹ́ Wọn yóò tún gbé wa dìde ni?

:48

Ṣé àti àwọn bàbá wa, àwọn ẹni àkọ́kọ́?”

:49

Sọ pé: “Dájúdájú àwọn ẹni àkọ́kọ́ àti àwọn ẹni Ìkẹ́yìn,

:50

dájúdájú A óò kó wọn jọ papọ̀ ní àkókò ọjọ́ kan tí A ti mọ̀.”

:51

Lẹ́yìn náà, dájúdájú ẹ̀yin olùṣìnà, olùpe-òdodo-nírọ́,

:52

dájúdájú ẹ̀yin máa jẹ nínú igi zaƙƙūm (igi iwọ).

:53

Ikùn yín sì máa kún bámúbámú fún (jíjẹ) igi náà.

:54

Ẹ̀yin yó sì máa mu omi tó gbóná parí lé e lórí.

:55

Ẹ̀yin yóò máa mu ún ní ìmumi ràkúnmí tí òǹgbẹ ń gbẹ.

:56

Èyí ni n̄ǹkan àlejò wọn ní Ọjọ́ ẹ̀san.

:57

Àwa l’A ṣẹ̀dá yín. Kí ni kò jẹ́ kí ẹ gbàgbọ́ ní òdodo!

:58

Ẹ sọ fún Mi nípa àtọ̀ tí ẹ̀ ń dà jáde (sínú àpòlùkẹ́),

:59

ṣé ẹ̀yin lẹ ṣẹ̀dá rẹ̀ ni tàbí Àwa l’A ṣẹ̀dá rẹ̀?

:60

Àwa l’A yan kádàrá (ọjọ́) ikú fún gbogbo yín. Àwa kò sì lè kágara

:61

láti yí irú yín padà (láti erùpẹ̀ sí alààyè), kí á sì tun yín dá (ní ọ̀tun) sínú ohun tí ẹ kò mọ̀.

:62

Ẹ kúkú mọ ìṣẹ̀dá àkọ́kọ́ (pé láti ibi àìsí ni ẹ ti di alààyè), ẹ kò ṣe lo ìrántí?

:63

Ẹ sọ fún Mi nípa n̄ǹkan tí ẹ̀ ń gbìn sínú ilẹ̀,

:64

ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń jẹ́ kí ó hù jáde tàbí Àwa l’À ń jẹ́ kí ó hù jáde?

:65

Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá sọ ọ́ di gbígbẹ, ẹ̀yin yó sì máa ṣèèmọ̀ (tí ẹ óò máa ká àbámọ̀).

:66

(Ẹ̀yin yó sì wí pé:) “Dájúdájú àwa ti di onígbèsè.”

:67

(Àwọn mìíràn yó sì wí pé:) “Rárá o! Wọ́n ṣe ìkórè oko ní èèwọ̀ fún wa ni.”

:68

Ẹ sọ fún mi nípa omi tí ẹ̀ ń mu,

:69

ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀ láti inú ẹ̀ṣújò ni tàbí Àwa l’À ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀?

:70

Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá ṣe é ní omi tó móró. Ẹ ò ṣe máa dúpẹ́?

:71

Ẹ sọ fún Mi nípa iná tí ẹ̀ ń dá,

:72

ṣé ẹ̀yin l’ẹ ṣẹ̀dá igi rẹ̀ ni tàbí Àwa ni Aṣẹ̀dá?

:73

Àwa ṣe iná ayé ní ìrántí (fún Iná ọ̀run) àti n̄ǹkan èlò fún àwọn onírìn-àjò.

:74

Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.

:75

Nítorí náà, Mò ń fi àwọn àyè tí ìkọ̀ọ̀kan gbólóhùn al-Ƙur’ān wà nínú sánmọ̀ búra.1

:76

Dájúdájú ìbúra ńlá ni, tí ẹ bá mọ̀.

:77

Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni n̄ǹkan kíké alápọ̀n-ọ́nlé.

:78

Ó wà nínú Tírà kan tí wọ́n ń fi ààbò bò (ìyẹn Laohul-Mahfūṭḥ).

:79

Kò sí ẹni tó lè fọwọ́ kàn án (ní ọ̀dọ̀ Allāhu) àfi àwọn ẹni mímọ́ (ìyẹn, àwọn mọlāika).

:80

Wọ́n sọ al-Ƙur’ān kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀dá.

:81

Nítorí náà, ṣé ọ̀rọ̀ (al-Ƙur’ān) yìí l’ẹ̀ ń pè ní irọ́?

:82

Ẹ sì ń sọ ìdúpẹ́ arísìkí yín di pé dájúdájú ẹ̀ ń pe òdodo ní irọ́.1

:83

Kí ni ó máa ti rí (fún yín) nígbà tí ẹ̀mí (yín) bá dé ọ̀nà ọ̀fun,

:84

tí ẹ̀yin yó sì máa wò bọ̀ọ̀ nígbà yẹn?

:85

Àwa sì súnmọ́ ọn ju ẹ̀yin lọ, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò ríran.1

:86

Ẹ̀yin kò ṣe jẹ́ ẹni tí A ò níí gbẹ̀san lára rẹ̀,

:87

kí ẹ sì dá (ẹ̀mí tí ó fẹ́ bọ́) padà, tí ẹ bá jẹ́ olódodo.

:88

Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn alásùn-únmọ́ (Wa),

:89

ìsinmi, èsè tó dára àti Ọgbà Ìdẹ̀ra (ni tirẹ̀).

:90

Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún,

:91

àlàáfíà ni fún ọ láààrin àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.

:92

Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn olùpe-òdodo-nírọ́, àwọn olùṣìnà,

:93

n̄ǹkan àlejò (wọn) ni omi tó gbóná parí

:94

àti wíwọ inú iná Jẹhīm.

:95

Dájúdájú èyí, òhun ni òdodo tó dájú.

:96

Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.